Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 31:24-32 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. “Bí ó bá ṣe pé mo fi wúrà ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé mi,tàbí tí mo bá wí fún fàdákà dídára pé, ‘Ìwọ ni ààbò mi;’

25. Bí mo bá yọ̀ nítorí ọrọ̀ mí pọ̀, àtinítorí ọwọ́ mi dẹ lọ́pọ̀lọpọ̀;

26. Bí mo bá bojú wo oòrùn nígbà tíń ràn, tàbí òṣùpá tí ń ràn nínú ìtànmọ́lẹ̀,

27. Bí a bá tàn ọkàn mi jẹ: Láti fíẹnu mi kò ọwọ́ mi:

28. Èyí pẹ̀lú ni ẹ̀ṣẹ̀ ti àwọn Onidàájọ́ níbẹ̀wò. Nítorí pé èmí yóò jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run tí ó wà lókè.

29. “Bí ó bá ṣepé mo yọ̀ sì ìparun ẹnití ó korìíra mi. Tàbí bí mo bá sì gbéra sókè, nígbà tí ibi bá a.

30. Bẹ́ẹ̀ èmí kò sì jẹ ẹnu mi ki ó ṣẹ̀nípa fífi ègún sí ọkàn rẹ̀.

31. Bí àwọn ènìyàn inú àgọ́ mi kò bálè wí pé, ta ni kò ì tí ì jẹ ẹran rẹ̀ ní àjẹyó?

32. (Àléjò kò wọ̀ ni ìgboro rí; èmí síìlẹ̀kùn mi sílẹ̀ fún èrò.)

Ka pipe ipin Jóòbù 31