Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 31:16-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. “Bí mo bá fa ọwọ́ sẹ́yìn fún ìfẹ́inú talákà, tàbí bí mo bá sì mú kí ojú opó di aláìríran,

17. Tàbí tí mo bá nìkan bu òkèlè mijẹ, tí aláìní baba kò jẹ nínú rẹ̀;

18. Nítorí pé láti ìgbà èwe mi wá nia ti tọ́ ọ dàgbà pẹ̀lú mi bí ẹnipé baba, èmi sì ń ṣe ìtọ́jú opó láti inú ìyá mi wá:

19. Bí èmi bá rí olùpọ́njú láìní aṣọ,tàbí talákà kan láìní ìbora;

20. Bí ọkàn rẹ̀ kò bá súre fún mi,tàbí bí ara rẹ̀ kò sì gbóná nípaṣẹ̀ irun àgùntàn mi;

21. Bí mo bá sì gbé ọwọ́ mi sókè síaláìní baba, nítorí pé mo rí ìrànlọ́wọ́ mi ní ẹnu ibodè,

22. Ǹjẹ́, ní apá mi kí o wọ́n kúrò níọkọ́ èjìká rẹ̀, kí apá mi kí ó sì ṣẹ́ láti egungun rẹ̀ wá.

23. Nítorí pé ìparun láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́runwá ni ẹ̀rù-ńlá fún mi, àti nitorí Ọláńlá rẹ̀ èmi kò le è dúró.

24. “Bí ó bá ṣe pé mo fi wúrà ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé mi,tàbí tí mo bá wí fún fàdákà dídára pé, ‘Ìwọ ni ààbò mi;’

25. Bí mo bá yọ̀ nítorí ọrọ̀ mí pọ̀, àtinítorí ọwọ́ mi dẹ lọ́pọ̀lọpọ̀;

26. Bí mo bá bojú wo oòrùn nígbà tíń ràn, tàbí òṣùpá tí ń ràn nínú ìtànmọ́lẹ̀,

27. Bí a bá tàn ọkàn mi jẹ: Láti fíẹnu mi kò ọwọ́ mi:

28. Èyí pẹ̀lú ni ẹ̀ṣẹ̀ ti àwọn Onidàájọ́ níbẹ̀wò. Nítorí pé èmí yóò jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Ọlọ́run tí ó wà lókè.

29. “Bí ó bá ṣepé mo yọ̀ sì ìparun ẹnití ó korìíra mi. Tàbí bí mo bá sì gbéra sókè, nígbà tí ibi bá a.

30. Bẹ́ẹ̀ èmí kò sì jẹ ẹnu mi ki ó ṣẹ̀nípa fífi ègún sí ọkàn rẹ̀.

31. Bí àwọn ènìyàn inú àgọ́ mi kò bálè wí pé, ta ni kò ì tí ì jẹ ẹran rẹ̀ ní àjẹyó?

Ka pipe ipin Jóòbù 31