Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 31:13-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. “Tí mo bá sì se àìka ọ̀ràn ìránṣẹ́kùnrinmi tàbí ìránṣẹ́bìnrin mi sí, nígbà tí wọ́n bá ń bá mi jà;

14. Kí ni èmi ó ha ṣe nígbà tí Ọlọ́runbá dìde? Nígbà tí ó bá sì ṣe ìbẹ̀wò, ohùn kí ni èmi ó dá?

15. Ẹni tí ó dá mi ní inú kọ́ ni ó dá a?Ẹnìkan náà kí ó mọ wá ní inú ìyá wa?

16. “Bí mo bá fa ọwọ́ sẹ́yìn fún ìfẹ́inú talákà, tàbí bí mo bá sì mú kí ojú opó di aláìríran,

17. Tàbí tí mo bá nìkan bu òkèlè mijẹ, tí aláìní baba kò jẹ nínú rẹ̀;

18. Nítorí pé láti ìgbà èwe mi wá nia ti tọ́ ọ dàgbà pẹ̀lú mi bí ẹnipé baba, èmi sì ń ṣe ìtọ́jú opó láti inú ìyá mi wá:

19. Bí èmi bá rí olùpọ́njú láìní aṣọ,tàbí talákà kan láìní ìbora;

20. Bí ọkàn rẹ̀ kò bá súre fún mi,tàbí bí ara rẹ̀ kò sì gbóná nípaṣẹ̀ irun àgùntàn mi;

Ka pipe ipin Jóòbù 31