Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 31:1-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “Mo ti bá ojú mi dá májẹ̀mu,èmi yó ha ṣe tẹjú mọ́ wúndíá?

2. Nítórí pé kí ni ìpín Ọlọ́run láti ọ̀run wá?Tàbí kí ni ogún Olódùmárè láti òkè ọ̀run wá.

3. Kò ṣe pé àwọn ènìyàn búburú niìparun wà fún, àti àjàkálẹ̀àrùn fún àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀?

4. Òun kò ha ri ipa ọ̀nà mi, òun kòha sì ka gbogbo ìṣíṣẹ̀ mi?

5. “Bí ó bá ṣepé èmi bá fi àìṣòótọ́ rìn,tàbí tí ẹsẹ̀ mi sì yára sí ẹ̀tàn;

6. (Jẹ́ kí Ọlọ́run wọ̀n mí nínú ìwọ̀nòdodo, kí Ọlọ́run le mọ ìdúró ṣinṣin mi.)

7. Bí ẹṣẹ̀ mí bá yà kúrò lójú ọ̀nà, tíàyà mí sì tẹ̀lé ipa ojú mi, tàbíbí àbàwọ́n kan bá sì lẹ̀mọ́ mi ní ọwọ́,

8. Ǹjẹ́ kí èmi kí ó gbìn kí ẹlòmìírànkí ó sì mújẹ, àní kí a fa irú ọmọ mi tu.

9. “Bí àyà mi bá di fífà sípasẹ̀ obinrin kan,tàbí bí mo bá lọ í ba de ènìyàn ní ẹnu ọ̀nà ilé aládùúgbò mi,

10. Ṣùgbọ́n kí àyà mi kí ó lọ ọlọ fúnẹlòmíràn, kí àwọn ẹlòmíràn kí ó tẹ̀ ara wọn ní ara rẹ̀.

11. Nítorí pé yóò jẹ́ ohun ìtìjú àníẹ̀ṣẹ̀ tí a ó ṣe onídàájọ́ rẹ̀

12. Nítorí pé iná ní èyí tí ó jó dé ibiìparun, tí ìbá sì fa gbòǹgbòohun ìbísí mi gbogbo tu.

13. “Tí mo bá sì se àìka ọ̀ràn ìránṣẹ́kùnrinmi tàbí ìránṣẹ́bìnrin mi sí, nígbà tí wọ́n bá ń bá mi jà;

Ka pipe ipin Jóòbù 31