Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 30:4-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Àwọn ẹni tí ń já ewé iyọ̀ ní ẹ̀báìgbẹ́; gbogbo igikígi ni ounjẹ jíjẹ wọn.

5. A lé wọn kúrò láàrin ènìyàn,àwọn ènìyàn sì pariwo lé wọn lórí bí ẹní pariwo lé olè lórí.

6. A mú wọn gbe inú pàlàpálá òkùtaàfonífojì, nínú ihò ilẹ̀ àti ti òkúta.

7. Wọ́n ń dún bí ẹranko ní àárinìgbẹ́, wọ́n kó ara wọn jọpọ̀ ní abẹ́ èṣìsì.

8. Àwọn ọmọ ẹni tí òye kò yé, àníàwọn ọmọ lásán, a sì lé wọn jáde kúrò ní orí ilẹ̀.

9. “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, àwọn ọmọ wọn ńfi mí ṣe ẹlẹ́yà nínú orin; àníèmi di ẹni ìsọ̀rọ̀ sí láàrin wọn.

10. Wọ́n kórìíra mi; wọ́n sá kúrò jìnnàsími, wọn kò sì bìkítà láti tutọ́ sími lójú.

11. Nítorí Ọlọ́run ti tú okùn ìyè mi,ó sì pọ́n mi lójú; àwọn pẹ̀lú sì dẹ ìjánu níwájú mi.

12. Àwọn ènìyàn lásán dìde ní apáọ̀tún mi; wọ́n tì ẹsẹ̀ mikúrò, wọ́n sì la ipa ọ̀nà ìparun sílẹ̀ dèmí.

13. Wọ́n da ipa ọ̀nà mi rú; wọ́n sìsọ ìparun mi di púpọ̀, àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́.

14. Wọ́n ya sími bí i omi tí ó yagbuuru; ní ariwo ńlá ni wọ́n kó ara wọn ká tì sí mi.

15. Ẹ̀rù ńlá bà mí; wọ́n lépa ọkànmi bí ẹ̀fúùfù, àlàáfíà mi sì kọjá lọ bí àwọ̀ sánmọ̀.

16. “Àti nísinsin yìí ọkàn mí sì dà jádesíi; ọjọ́ ìpọ́njú mi dì mí mú.

17. Òru gún mi nínú egungun mi, ìyítí ó bù mí jẹ kò sì sinmi.

18. Nípa agbára ńlá rẹ̀ Ọlọ́run wà bí aṣọ ìbora fún mi, ó sì lẹ̀mọ́mi ní ara yíká bí ọrùn aṣọ ìlekè mi.

19. Ọlọ́run ti mú mi lọ sínú ẹrẹ̀,èmi sì dàbí eruku àti eérú.

20. “Èmi ké pè ọ́ ìwọ Ọlọ́run ṣùgbọ́n,ìwọ kò dámi lóhùn; èmi dìde dúró ìwọ sì wò mí lásán.

Ka pipe ipin Jóòbù 30