26. Nígbà tí mo fojú sọ́nà fún àlàáfíà, ibi sì dé;nígbà tí mo dúró de ìmọ́lẹ̀, òkùnkùn sì dé.
27. Ikùn mí n ru kò sì sinmi; Ọjọ́ìpọ́njú ti dé bámi.
28. Èmí ń rìn kiri nínú ọ̀fọ̀, ṣùgbọ́nkì í ṣe nínú òòrùn; èmi dìdedúró ní àwùjọ mo sì kígbé fún ìrànlọ́wọ́.
29. Èmi ti di arákùnrin ìkòokò, èmidi ẹgbẹ́ àwọn ògòǹgò.
30. Àwọ̀ mi di dúdú ó sì ń bọ́wọ̀;egungun mi sì jórun fún oru.