Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 30:1-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí,àwọn tí mo gbà ní àbúrò ń fi míṣe ẹlẹ́yà, baba ẹni tí èmi kẹ́gànláti tò pẹ̀lú àwọn ajá agbo-ẹran mi.

2. Kí ni ìwúlò agbára ọwọ́ wọn sími,níwọ̀n ìgbà tí agbára wọn ti fi wọ́n sílẹ̀?

3. Wọ́n rù nítorí àìní àti ìyànwọ́n ń rìn káàkiri ní ilẹ̀ gbígbẹní ibi ìkọsílẹ̀ ní òru.

4. Àwọn ẹni tí ń já ewé iyọ̀ ní ẹ̀báìgbẹ́; gbogbo igikígi ni ounjẹ jíjẹ wọn.

5. A lé wọn kúrò láàrin ènìyàn,àwọn ènìyàn sì pariwo lé wọn lórí bí ẹní pariwo lé olè lórí.

6. A mú wọn gbe inú pàlàpálá òkùtaàfonífojì, nínú ihò ilẹ̀ àti ti òkúta.

7. Wọ́n ń dún bí ẹranko ní àárinìgbẹ́, wọ́n kó ara wọn jọpọ̀ ní abẹ́ èṣìsì.

8. Àwọn ọmọ ẹni tí òye kò yé, àníàwọn ọmọ lásán, a sì lé wọn jáde kúrò ní orí ilẹ̀.

9. “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, àwọn ọmọ wọn ńfi mí ṣe ẹlẹ́yà nínú orin; àníèmi di ẹni ìsọ̀rọ̀ sí láàrin wọn.

10. Wọ́n kórìíra mi; wọ́n sá kúrò jìnnàsími, wọn kò sì bìkítà láti tutọ́ sími lójú.

11. Nítorí Ọlọ́run ti tú okùn ìyè mi,ó sì pọ́n mi lójú; àwọn pẹ̀lú sì dẹ ìjánu níwájú mi.

12. Àwọn ènìyàn lásán dìde ní apáọ̀tún mi; wọ́n tì ẹsẹ̀ mikúrò, wọ́n sì la ipa ọ̀nà ìparun sílẹ̀ dèmí.

13. Wọ́n da ipa ọ̀nà mi rú; wọ́n sìsọ ìparun mi di púpọ̀, àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́.

14. Wọ́n ya sími bí i omi tí ó yagbuuru; ní ariwo ńlá ni wọ́n kó ara wọn ká tì sí mi.

Ka pipe ipin Jóòbù 30