Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 3:19-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Àti èwe àti àgbà wà níbẹ̀,ẹrú sì di òmìnira kúrò lọ́wọ́ olówó rẹ̀.

20. “Nítorí kí ni a ṣe fi ìmọ́lẹ̀ fún òtòsì,àti ìyè fún ọlọ́kan kíkorò,

21. tí wọ́n dúró de ikú, ṣùgbọ́n òun kò wá,tí wọ́n wálẹ̀ wá a jù fún ìṣúra tí a bò mọ́lẹ̀ pamọ́.

22. Ẹni tí ó yọ̀ gidigidi,tí inú wọ́n sì dùn nígbà tí wọ́n wá ibojì òkú rí?

23. Kí ni a fi ìmọ́lẹ̀ fún ẹni tí ọ̀nà rẹ̀fi ara pamọ́ fúntí Ọlọ́run sì ṣọgbà yí wọn ká?

24. Nítorí pé èémí-ẹ̀dùn wà ṣáájú oúnjẹ mi;ikérora mi sì tú jáde bí omi.

25. Nítorí pé ohun náà tí mo bẹ̀rù gidigidi ni ó dé bá mi yìí,àti ohun tí mo fòyà rẹ̀ bá mi ó sì ṣubú lù mí.

Ka pipe ipin Jóòbù 3