Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 29:2-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. “Áà! ìbá ṣe pé èmi wà bí ìgbà oṣù tíó kọjá, bí ọjọ́ tí Ọlọ́run pamímọ́;

3. Nígbà tí fìtílà rẹ tàn sí mi ní orí,àti nípa ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ èmi rìn nínú òkùnkùn já;

4. Bí mo tirí nígbà ọ̀dọ́ mi, nígbàtí ọ̀rẹ́ Ọlọ́run tímọ́tímọ́ bùkún ilé mi

5. Nígbà tí Olódùmarè wà pẹ̀lú mi,nígbà tí àwọn ọmọ mi wà yí mi ká;

6. Nígbà tí èmi fi òrí àmọ́ n wẹ ìsísẹ̀ mi,àti tí àpata ń tú ìsàn òróró jáde fún mi wá.

7. “Nígbà tí mo jáde la àárin ìlú lọ síẹnu ibodè, nígbà tí mo tẹ́ ìtẹ́ mi ní ìgboro,

8. Nígbà náà ni àwọn ọmọkùnrin rími, wọ́n sì sápamọ́, àwọn àgbà dìde dúró ní ẹṣẹ̀ wọn;

9. Àwọn ọmọ aládé dákẹ́ ọ̀rọ̀ sí sọ,wọn a sì fí ọwọ́ wọn lé ẹnu;

10. Àwọn ọmọ ọlọ́lá dákẹ́, ahọ́n wọnsì lẹ̀mọ́ èrìgì ẹnu wọn.

11. Nígbà tí etí gbọ́, ó sì súrefún mi,àti nígbà tí ojú sì rí mi, ó jẹ́rìí mi;

12. Nítorí mo gbà talákà tí n fẹ́ ìrànlọ́wọ́,àti aláìní baba, tí kò sí olùrànlọ́wọ́ fún un

13. Ẹni tí ó ń kìlọ̀ súre fún mi, èmisì mú àyà opó kọrin fún ayọ̀.

14. Èmi sì mú òdodo wọ̀ bí aṣọ, ẹ̀tọ́mi dà bí aṣọ ìgúnwà àti adé ọba.

Ka pipe ipin Jóòbù 29