Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 24:7-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Ní hòòhò ni wọn má a sùn láìní aṣọ,tí wọn kò ní ìbora nínú òtútù.

8. Ọ̀wàrà òjò òkè ńlá sì pa wọ́n,wọ́n sì lẹ̀mọ́ àpáta nítorí tí kò sí ààbò.

9. Wọ́n já ọmọ aláìní baba kúrò níẹnu ọmú, wọ́n sì gbà ọmọ talákà. Nítorí gbèsè

10. Wọ́n rìn kiri níhòòhò láìní aṣọ;àwọn tí ebi ń pa rẹrù ìdì ọkà,

11. Àwọn ẹni tí ń fún òróró nínúàgbàlá wọn, tí wọ́n sì ń tẹ ìfúntíàjàrà, òǹgbẹ sì ń gbẹ wọn.

12. Àwọn ènìyàn ń kérora láti ìlú wá,ọkàn àwọn ẹni tí ó gbọgbẹ́kígbe sókè; fún ìrànlọ́wọ́ ṣíbẹ̀Ọlọ́run kò kíyèsí àṣìṣe náà.

13. “Àwọn ni ó wà nínú àwọn tí ó kọ̀ìmọ́lẹ̀; Wọn kò mọ̀ ipa ọ̀nà rẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni wọn kò dúró nípa ọ̀nà rẹ̀.

14. Panipani a dìde ní àfẹ̀mọ́júmọ́,a sì pa talákà àti aláìní, àti ní òru a di olè.

15. Ojú alágbèrè pẹ̀lú dúró deàfẹ̀mọ́júmọ́ ọjọ́; ‘Ó ní, ojúẹnìkan kì yóò rí mi;’ ó sì fi ìbòjú bojú rẹ̀.

16. Ní òkùnkùn wọn á rúnlẹ̀ wọlé,tí wọ́n ti fi ojú sọ fún ara wọnní ọ̀sán, wọn kò mọ̀ ìmọ́lẹ̀.

17. Nítorí pé bí òru dúdú ní òwúrọ̀fún gbogbo wọn; nítorí tí wọn sì mọ̀ ìbẹ̀rù òkùnkùn.

18. “Ó yára lọ bí ẹni lójú omi; ìpín wọn ní ilé ayé ni a ó parun;òun kò rìn mọ́ ní ọ̀nà ọgbà àjàrà.

19. Ọ̀dá àti òru ní ímú omi ojọ-didi gbẹ, bẹ́ẹ̀ní isà òkú írun àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.

Ka pipe ipin Jóòbù 24