Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 23:3-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Áà! èmi ìbá mọ ibi tí èmí ìbá wáỌlọ́run rí, kí èmí kí ó tọ̀ ọ́ lọ sí ibùgbé rẹ̀!

4. Èmi ibá sì to ọ̀ràn náà níwájú rẹ̀,ẹnu mi ìbá sì kún fún àròyé.

5. Èmi ìbá sì mọ ọ̀rọ̀ tí òun ìbá fi dámi lóhùn; òye ohun tí ìbá wí a sì yé mi.

6. Yóò ha fi agbára ńlá bá mi wíjọ́ bí?Àgbẹdọ̀, kìkì pé òun yóò sì kíyèsí mi.

7. Níbẹ̀ ni olódodo le è bá awíjọ́, níwájú rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni èmi yóòsì bọ́ ni ọwọ́ onídájọ́ mi láéláé.

8. “Sì wòó, bí èmi bá lọ sí iwájú,òun kò sí níbẹ̀, àti sí ẹ̀yìn, èmi kò sì rí òye rẹ̀:

9. Ni apá òsì bí ó bá ṣiṣẹ́ níbẹ̀, èmikò rí i, ó fi ara rẹ̀ pamọ́ ni apaọ̀tún, tí èmi kò le è rí i.

10. Ṣùgbọ́n òun mọ ọ̀nà tí èmi ń tọ̀,nígbà tí ó bá dán mí wò, èmi yóò jáde bí wúrà.

Ka pipe ipin Jóòbù 23