Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 20:4-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. “Ìwọ kò mọ̀ èyí rí ní ìgbà àtijọ́,láti ìgbà tí a sọ ènìyàn lọ́jọ̀ silẹ̀ ayé,

5. Pé, orin ayọ̀ ènìyàn búburú, ìgbàkúkúrú ni, àti pé, ní ìṣẹ́jú kan ní ayọ̀ àgàbàgebè?

6. Bí ọláńlá rẹ̀ tilẹ̀ gòkè dé ọ̀run, tiori rẹ̀ sì kan àwọsánmà;

7. Ṣùgbọ́n yóò ṣègbé láéláé bí ìgbẹ́ara rẹ̀; àwọn tí ó ti rí i rí yóò wí pé, ‘Òun ha dà?’

8. Yóò fò lọ bí àlá, a kì yóò sì rí i,àní a ó lé e lọ bi ìran òru.

9. Ojú tí ó ti rí i rí kì yóò sì rí i mọ́,bẹ́ẹ̀ ni ibùjókòó rẹ̀ kì yóò sì ri i mọ́.

10. Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wá àti ríojú-rere lọ́dọ̀ talákà, ọwọ́ rẹ̀ yóò sì kó ọrọ̀ wọn padà.

11. Egungun rẹ̀ kún fún agbára ìgbàèwe rẹ̀, tí yóò bá a dùbúlẹ̀ nínú erùpẹ̀.

12. “Bí ìwà búburú tilẹ̀ dún ní ẹnurẹ̀, bí ó tilẹ̀ pa á mọ́ nísàlẹ̀ ahọ́n rẹ̀,

13. bí ó tilẹ̀ dá a sí, tí kò si kọ̀ ọ́ sílẹ̀,tí ó pa á mọ́ síbẹ̀ ní ẹnu rẹ̀,

14. Ṣùgbọ́n oúnjẹ rẹ̀ nínú ikùn rẹ̀ tiyípadà, ó jásí òróró pamọ́lẹ̀ nínú rẹ̀;

Ka pipe ipin Jóòbù 20