20. “Nítorí òun kò mọ̀ ìwà pẹ̀lẹ́ nínúara rẹ̀, kì yóò sì gbà nínú èyí tí ọkán rẹ̀ fẹ́ sílẹ̀.
21. Ohun kan kò kù fún jíjẹ́ rẹ̀;Nitorí náà ọ̀rọ̀ rẹ̀ kì yóò dúró pẹ́.
22. Nínú ànító rẹ̀, ìdààmú yóò dé bá a;àwọn ènìyàn búburú yóò dáwọ́ jọ lé e lórí.
23. Yóò sì ṣe, nígbà tí ó bá fẹ́ jẹunỌlọ́run yóò fà ríru ìbínú rẹ̀ sí í lórí,nígbà tó bá ń jẹun lọ́wọ́,yóò sì rọ òjò ìbínú rẹ̀ lé e lórí.
24. Yóò sá kúrò lọ́wọ́ ohun ogunìrìn; ọrun akọ irin ní yóò ta a po yọ.