Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 20:2-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. “Nítorí náà ní ìro inú mi dá mi lóhùn,àti nítorí èyí náà ní mo sì yára si gidigidi.

3. Mo ti gbọ́ ẹ̀san ẹ̀gàn mi, ẹ̀mí òyemi sì dá mi lóhùn.

4. “Ìwọ kò mọ̀ èyí rí ní ìgbà àtijọ́,láti ìgbà tí a sọ ènìyàn lọ́jọ̀ silẹ̀ ayé,

5. Pé, orin ayọ̀ ènìyàn búburú, ìgbàkúkúrú ni, àti pé, ní ìṣẹ́jú kan ní ayọ̀ àgàbàgebè?

6. Bí ọláńlá rẹ̀ tilẹ̀ gòkè dé ọ̀run, tiori rẹ̀ sì kan àwọsánmà;

7. Ṣùgbọ́n yóò ṣègbé láéláé bí ìgbẹ́ara rẹ̀; àwọn tí ó ti rí i rí yóò wí pé, ‘Òun ha dà?’

8. Yóò fò lọ bí àlá, a kì yóò sì rí i,àní a ó lé e lọ bi ìran òru.

9. Ojú tí ó ti rí i rí kì yóò sì rí i mọ́,bẹ́ẹ̀ ni ibùjókòó rẹ̀ kì yóò sì ri i mọ́.

10. Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wá àti ríojú-rere lọ́dọ̀ talákà, ọwọ́ rẹ̀ yóò sì kó ọrọ̀ wọn padà.

11. Egungun rẹ̀ kún fún agbára ìgbàèwe rẹ̀, tí yóò bá a dùbúlẹ̀ nínú erùpẹ̀.

12. “Bí ìwà búburú tilẹ̀ dún ní ẹnurẹ̀, bí ó tilẹ̀ pa á mọ́ nísàlẹ̀ ahọ́n rẹ̀,

13. bí ó tilẹ̀ dá a sí, tí kò si kọ̀ ọ́ sílẹ̀,tí ó pa á mọ́ síbẹ̀ ní ẹnu rẹ̀,

14. Ṣùgbọ́n oúnjẹ rẹ̀ nínú ikùn rẹ̀ tiyípadà, ó jásí òróró pamọ́lẹ̀ nínú rẹ̀;

15. Ó ti gbé ọrọ̀ mì, yóò sì tún bí ijáde; Ọlọ́run yóò pọ̀ ọ́ yọ jáde láti inú rẹ̀ wá.

16. Ó ti fà oró pamọ́lẹ̀ múu; ahọ́ngúnte ní yóò pa á.

17. Kì yóò rí odò wọ̀n-ọn-nì, ìṣàn omi,odò tí ń sàn fún oyin àti ti òrí àmọ́.

18. Ohun tí ó ṣíṣẹ́ fún ni yóò mú unpadà, kí yóò sì gbé e mì; gẹ́gẹ́bí ọrọ̀ tí ó ní, kì yóò sì yọ̀ nínú rẹ̀.

19. Nítorí tí ó fi owó rẹ̀ ni talákà lára,ó sì ti kẹ́hìndà wọ́n;Nítorí ti ó fi agbára gbé ilé tí òun kò kọ́.

20. “Nítorí òun kò mọ̀ ìwà pẹ̀lẹ́ nínúara rẹ̀, kì yóò sì gbà nínú èyí tí ọkán rẹ̀ fẹ́ sílẹ̀.

21. Ohun kan kò kù fún jíjẹ́ rẹ̀;Nitorí náà ọ̀rọ̀ rẹ̀ kì yóò dúró pẹ́.

22. Nínú ànító rẹ̀, ìdààmú yóò dé bá a;àwọn ènìyàn búburú yóò dáwọ́ jọ lé e lórí.

Ka pipe ipin Jóòbù 20