Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 20:17-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Kì yóò rí odò wọ̀n-ọn-nì, ìṣàn omi,odò tí ń sàn fún oyin àti ti òrí àmọ́.

18. Ohun tí ó ṣíṣẹ́ fún ni yóò mú unpadà, kí yóò sì gbé e mì; gẹ́gẹ́bí ọrọ̀ tí ó ní, kì yóò sì yọ̀ nínú rẹ̀.

19. Nítorí tí ó fi owó rẹ̀ ni talákà lára,ó sì ti kẹ́hìndà wọ́n;Nítorí ti ó fi agbára gbé ilé tí òun kò kọ́.

20. “Nítorí òun kò mọ̀ ìwà pẹ̀lẹ́ nínúara rẹ̀, kì yóò sì gbà nínú èyí tí ọkán rẹ̀ fẹ́ sílẹ̀.

21. Ohun kan kò kù fún jíjẹ́ rẹ̀;Nitorí náà ọ̀rọ̀ rẹ̀ kì yóò dúró pẹ́.

22. Nínú ànító rẹ̀, ìdààmú yóò dé bá a;àwọn ènìyàn búburú yóò dáwọ́ jọ lé e lórí.

23. Yóò sì ṣe, nígbà tí ó bá fẹ́ jẹunỌlọ́run yóò fà ríru ìbínú rẹ̀ sí í lórí,nígbà tó bá ń jẹun lọ́wọ́,yóò sì rọ òjò ìbínú rẹ̀ lé e lórí.

24. Yóò sá kúrò lọ́wọ́ ohun ogunìrìn; ọrun akọ irin ní yóò ta a po yọ.

25. O fà á yọ, ó sì jáde kúrò lára; idàdídán ní ń jáde láti inú òróòrowá: Ẹ̀rù ńlá ń bẹ ní ara rẹ̀.

26. Òkùnkùn biribiri ní a ti pamọ́fún ìṣúra rẹ̀; iná ti a kò fẹ́ níyóò jó o run: yóò sì jẹ èyí tí ókù nínú àgọ́ rẹ̀ run.

27. Ọ̀run yóò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn, ayé yóòsì dìde dúró sí i.

Ka pipe ipin Jóòbù 20