Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 18:1-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ígbà náà ni Bílídádì, ará Ṣúà, dáhùn, ó sì wí pé:

2. “Nígbà wo ni ẹ̀yin yóò tó fi ìdí ọ̀rọ̀tì; ẹ rò ó, nígbẹ̀yìn rẹ̀ ni àwa ó tó máa sọ

3. Nítorí kí ni a ṣe ń kà wá sí bíẹranko, tí a sì ń kà wá si bí ẹni ẹ̀gàn ní ojú yín?

4. Ìwọ fa ara rẹ ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ nínúìbínú rẹ̀; kí a ha kọ ayé sílẹ̀nítorí rẹ̀ bi? Tàbí kí a sí àpáta kúrò ní ipò rẹ̀?

5. “Nítòótọ́ ìmọ́lẹ̀ ènìyàn búburú ni aó pa kúrò, Ọ̀wọ́ iná rẹ̀ kì yóò sì tan ìmọ́lẹ̀.

6. Ìmọ́lẹ̀ yóò di òkùnkùn nínú àgọ́rẹ̀, fìtílà ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ni a ó sì pa pẹ̀lú.

7. Ìrìn ẹṣẹ̀ agbára rẹ̀ yóò di fífọn;ìmọ́lẹ̀ òun tìkárarẹ̀ ni yóò bí i ṣubú.

8. Nípa ẹ̀ṣẹ̀ òun tìkararẹ̀ ó ti bọ́ sínúàwọ̀n, ó sì rìn lóri okùn dídẹ.

9. Tàkúté ni yóò mú un ní gìgísẹ̀,àwọn àwọ̀n tí a dẹ yóò sì ṣẹ́gun rẹ̀.

10. A dẹkùn sílẹ̀ fún un lórí ilẹ̀, a sìwà ọ̀fìn fún un lojú ọ̀nà.

11. Ẹ̀rù ńlá yóò bà á ní ìhà gbogbo,yóò sì lé e dé ẹsẹ̀ rẹ̀.

12. Àìlera rẹ̀ yóò di pipa fún ebi,ìparun yóò dìde dúró sí i nígbà tí ó bá ṣubú.

13. Yóò jẹ ẹ̀yà ara rẹ̀; àkọ́bí ikú niyóò jẹ agbára rẹ̀ run.

14. A ó fà á tu kurò nínú àgọ́ tí ógbẹ́kẹ̀lé, a ó sì mú un tọ ọba ẹ̀rù ńlá nì lọ.

Ka pipe ipin Jóòbù 18