Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 16:2-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. “Èmi ti gbọ́ irú ohun pípọ̀ bẹ́ẹ̀ ríayọnilẹ́nu onítùnú ènìyàn ní gbogbo yín.

3. Ọ̀rọ̀ asán lè ni òpin? Tàbí nín ni ógbó ọ láyà tí ìwọ fi dáhùn?

4. Èmi pẹ̀lú le sọ bí ẹ̀yin; bí ọkànyín bá wà ní ipò ọkàn mi, èmile íkọ ọ̀rọ̀ pọ̀ si yin ni ọ̀run, èmi a sì mi orí mi sí i yín.

5. Èmi ìbá fi ọ̀rọ̀ ẹnu mi gbà yín niìyànjú, àti ṣíṣí ètè mi ìbá sì tu ìbìnújẹ́ yín.

6. “Bí èmi tilẹ̀ sọ̀rọ̀, ìbìnújẹ́ mi kò tù;bí mo sì tilẹ̀ dákẹ́, níbo ni ìtùnú mí dé?

7. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó dá milágara; Ìwọ (Ọlọ́run) mú gbogbo ẹgbẹ́ mi takété.

8. Ìwọ sì fi ìkiyẹ̀jẹ kùn mí lára, tí ójẹ́rìí tì mí; àti rírù tí ó yọ lára mi, ó jẹ́rìí lòdì sí ojú mi.

9. Ọlọ́run fi Ìbínú rẹ̀ fà mí ya, ósì ṣọ̀tá mi; ó pa eyín rẹ̀ keke sími, ọ̀ta mi sì gbójú rẹ̀ sí mi.

10. Wọ́n ti fi ẹnu wọn yán sí mi;Wọ́n gbá mi ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ ni ìgbáẹ̀gàn; Wọ́n kó ara wọn pọ̀ sí mi.

11. Ọlọ́run ti fi mí lé ọwọ́ ẹnibúburú, ó sì mú mi ṣubú sí ọwọ́ ènìyàn ìkà.

Ka pipe ipin Jóòbù 16