Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 16:1-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ígbà náà ní Jóòbù dáhùn, ó sì wí pé:

2. “Èmi ti gbọ́ irú ohun pípọ̀ bẹ́ẹ̀ ríayọnilẹ́nu onítùnú ènìyàn ní gbogbo yín.

3. Ọ̀rọ̀ asán lè ni òpin? Tàbí nín ni ógbó ọ láyà tí ìwọ fi dáhùn?

4. Èmi pẹ̀lú le sọ bí ẹ̀yin; bí ọkànyín bá wà ní ipò ọkàn mi, èmile íkọ ọ̀rọ̀ pọ̀ si yin ni ọ̀run, èmi a sì mi orí mi sí i yín.

5. Èmi ìbá fi ọ̀rọ̀ ẹnu mi gbà yín niìyànjú, àti ṣíṣí ètè mi ìbá sì tu ìbìnújẹ́ yín.

6. “Bí èmi tilẹ̀ sọ̀rọ̀, ìbìnújẹ́ mi kò tù;bí mo sì tilẹ̀ dákẹ́, níbo ni ìtùnú mí dé?

7. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ó dá milágara; Ìwọ (Ọlọ́run) mú gbogbo ẹgbẹ́ mi takété.

8. Ìwọ sì fi ìkiyẹ̀jẹ kùn mí lára, tí ójẹ́rìí tì mí; àti rírù tí ó yọ lára mi, ó jẹ́rìí lòdì sí ojú mi.

9. Ọlọ́run fi Ìbínú rẹ̀ fà mí ya, ósì ṣọ̀tá mi; ó pa eyín rẹ̀ keke sími, ọ̀ta mi sì gbójú rẹ̀ sí mi.

10. Wọ́n ti fi ẹnu wọn yán sí mi;Wọ́n gbá mi ní ẹ̀rẹ̀kẹ́ ni ìgbáẹ̀gàn; Wọ́n kó ara wọn pọ̀ sí mi.

Ka pipe ipin Jóòbù 16