Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 15:4-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ìwọ ṣá ìbẹ̀rù tì, ìwọ sì dí àdúràlọ́nà níwájú Ọlọ́run.

5. Nítorí pé ẹnu ara rẹ̀ ni ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀rẹ̀, ìwọ sì yàn ahọ́n alárékérekè ni ààyò.

6. Ẹnu ara rẹ̀ ni ó dá lẹ́bi, kì í ṣe èmi;àní ètè ara rẹ̀ ni ó jẹ́rìí tì ọ́.

7. “Ìwọ ha íse ọkùnrin tí a kọ́ bi? Tabìa há dá ọ ṣáájú àwọn òkè?

8. Ìwọ gburòó àsírí Ọlọ́run rí, tàbíìwọ ha dá ọgbọ́n dúró sọ́dọ̀ ara rẹ?

9. Kí ni ìwọ mọ̀ tí àwa kò mọ̀? Òyekí ní ó yé ọ tí kò sí nínú wa?

10. Eléwú ogbó àti ògbólógbòóènìyàn wà pẹ̀lú wa, tí wọ́n gbójú baba rẹ lọ.

11. Ìtùnú Ọlọ́run ha kéré lọ́dọ̀ rẹ?Ọ̀rọ̀ kan sì ṣe jẹ́jẹ́ jù lọ́dọ̀ rẹ?

12. Èéṣe ti àyà rẹ fi ń dà ọ kiri,kí ni n mú ojú rẹ se wàìwàì.

13. Tí ìwọ fi yí ẹ̀mí rẹ padà lòdì síỌlọ́run, tí ó fi ń jẹ́ ki ọ̀rọ̀kọ́rọ̀kí ó máa bọ́ ní ẹnu rẹ̀ bẹ́ẹ̀?

14. “Kí ni ènìyàn tí ó fi mọ́? Àti ẹni tía tinú obìnrin bí tí yóò fi ṣe olódodo?

15. Kíyèsí i, òun (Ọlọ́run) kògbẹ́kẹ̀lé àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀,àní àwọn ọ̀run kò mọ́ ní ojú rẹ̀;

16. Ańbọ̀tórí ènìyàn, ẹni ìríra àtieléèérìí, tí ń mù ẹ̀ṣẹ̀ bi ẹní mú omi.

17. “Èmi ó fihàn ọ́: gbọ́ ti èmi; Èyí tíèmi sì rí, òun ni èmi ó sì sọ,

Ka pipe ipin Jóòbù 15