Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 15:23-35 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

23. Ó ń wò káàkiri fún oúnjẹ wí pé,níbo ní ó wà? Ó mọ̀ pé ọjọ́òkùnkùn súnmọ́ tòsí.

24. Ìpọ́njú pẹ̀lú ìrora ọkàn yóò mú unbẹ̀rù, wọ́n ó sì sẹ́gun rẹ̀ bi ọba ti ímúra ogun.

25. Nítorí pé ó ti nawọ́ rẹ̀ jáde lòdìsí Ọlọ́run, ó sì múra rẹ̀ le lòdì sí Olódùmáarè,

26. Ó súre, ó sì fi ẹ̀yìn giga, àní fiìké kòóko àpáta rẹ̀ tí ó nipọn kọlù ú.

27. “Nítorí tí òun fi ọ̀rá rẹ̀ bo ara rẹ̀lojú, o sì ṣe jabajaba ọ̀rá sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀.

28. Òun sì gbé inú ahoro ìlú ìtakété,àti nínú iléyílé tí ènìyàn kò gbémọ́, tí ó múra tán lati di àlàpà.

29. Òun kò lé ìlà, bẹ́ẹ̀ ohun ìní rẹ̀ kòlè dúró pẹ́; Bẹ́ẹ̀ kò lè mú pípé rẹ̀ dúró pẹ́ lórí ilẹ̀.

30. Òun kì yóò jáde kúrò nínúòkùnkùn; ọ̀wọ́ iná ni yóò jóẹ̀ka rẹ̀, àti nípaṣẹ̀ ẹ̀mí ẹnu rẹ̀ní yóò máa kọjá lọ kúrò.

31. Kí òun kí ó má ṣe gbẹ́kẹ̀le asán,kí ó má sì ṣe tan ara rẹ̀ jẹ.Nítorí pé asán ní yóò jásí èrè rẹ̀.

32. A ó mú un ṣẹ ṣáájú pípẹ́ ọjọ́ rẹ̀,ẹ̀ka rẹ̀ kì yóò sì tutù.

33. Yóò sì gbọ̀n àìpọ́n èṣo rẹ̀ dànù bí i àjàrà,yóò sì rẹ̀ ìyanna rẹ̀ nù bí i ti igi Ólífì.

34. Nítorí pé ayọ̀ àwọn àgàbàgebèyóò túká, iná ní yóò sì jó àgọ́ àwọn tí ó fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀.

35. Wọ́n lóyún ìwà ìkà, wọ́n sì bíẹ̀ṣẹ̀, ikùn wọn sì pèṣè ẹ̀tàn.”

Ka pipe ipin Jóòbù 15