Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 15:1-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ígbà náà ní Élífásì, ará Témà, dáhùn wí pé:

2. “Ọlọ́gbọ́n a máa sọ̀rọ̀ ìmọ̀ asán, kíó sì máa fi afẹ́fẹ́ ìlà oòrun kún ara rẹ̀ nínú?

3. Òun lè máa fi àròyé sọ̀rọ̀ tí kò níèrè, tàbí pẹ̀lú ọ̀rọ̀ nínú èyí tí kò lè fi ṣe rere?

4. Ìwọ ṣá ìbẹ̀rù tì, ìwọ sì dí àdúràlọ́nà níwájú Ọlọ́run.

5. Nítorí pé ẹnu ara rẹ̀ ni ó jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀rẹ̀, ìwọ sì yàn ahọ́n alárékérekè ni ààyò.

6. Ẹnu ara rẹ̀ ni ó dá lẹ́bi, kì í ṣe èmi;àní ètè ara rẹ̀ ni ó jẹ́rìí tì ọ́.

7. “Ìwọ ha íse ọkùnrin tí a kọ́ bi? Tabìa há dá ọ ṣáájú àwọn òkè?

8. Ìwọ gburòó àsírí Ọlọ́run rí, tàbíìwọ ha dá ọgbọ́n dúró sọ́dọ̀ ara rẹ?

9. Kí ni ìwọ mọ̀ tí àwa kò mọ̀? Òyekí ní ó yé ọ tí kò sí nínú wa?

10. Eléwú ogbó àti ògbólógbòóènìyàn wà pẹ̀lú wa, tí wọ́n gbójú baba rẹ lọ.

11. Ìtùnú Ọlọ́run ha kéré lọ́dọ̀ rẹ?Ọ̀rọ̀ kan sì ṣe jẹ́jẹ́ jù lọ́dọ̀ rẹ?

Ka pipe ipin Jóòbù 15