Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 13:11-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Ìwà ọlá rẹ̀ kì yóò bà yín lẹ́rù bí?Ìpayà rẹ̀ kì yóò pá yín láyà?

12. Ìrántí yín dàbí eérú;Ìlú odi yín ìlú odi amọ̀.

13. “Ẹ pa ẹnu yín mọ́ kúrò lára mi,kí èmi kí ó lè sọ̀rọ̀, ohun tí ńbọ̀ wá íbá mi, kí ó máa bọ̀.

14. Ǹjẹ́ nítorí kí ni èmi ṣe ń fi èyín mibu ẹran ara mi jẹ, Tí mo sì gbé ẹ̀mí mi lé ara mi lọ́wọ́?

15. Bí ó tilẹ̀ pa mí, síbẹ̀ èmi ó máa gbẹ́kẹ̀lé e;Ṣùgbọ́n èmi ó máa tẹnumọ́ ọ̀nà mi níwájú rẹ̀.

16. Èyí ni yóò sì ṣe ìgbàlà mi,Àgàbàgebè kì yóò wá síwájú rẹ̀.

17. Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu mi ní ìfàyàbalẹ̀, àti àṣọpé mí ni etí yín.

18. Wò ó nísinsin yìí, èmi ti làdí ọ̀ran mi sílẹ̀;èmi mọ̀ pé a ó dá mi láre.

19. Ta ni òun ti yóò bá mi ṣàròyé?Ǹjẹ́ nísinsìn yìí, èmi fẹ́ pa ẹnu mí mọ́, èmi ó sì jọ́wọ́ ẹ̀mi mi lọ́wọ́.

Ka pipe ipin Jóòbù 13