Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 12:7-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. “Ṣùgbọ́n nísínyìí bí àwọn ẹranko léèrè, wọn o kọ́ ọ ní ẹ̀kọ́,àti ẹyẹ ojú ọ̀run, wọn ó sì sọ fún ọ.

8. Tàbí ba ilẹ̀ àyé sọ̀rọ̀, yóò sì kọ́ ọ,àwọn ẹja inú òkun yóò sì sọ fún ọ.

9. Ta ni kò mọ̀ nínú gbogbo nǹkanwọ̀nyí pé, ọwọ́ Olúwa ni ó ṣe nǹkan yìí?

10. Ní ọwọ́ ẹni tí ẹ̀mí ohun alààyègbogbo gbé wà, Àti ẹ̀mí gbogbo aráyé.

11. Etí kì í dán ọ̀rọ̀ wò bí, Tàbí adùnẹnu kì í sì í tọ́ oúnjẹ rẹ̀ wò bí?

12. Àwọn arúgbó ni ọgbọ́n wà fún,Àti nínú gígùn ọjọ́ ni òye?

13. “Pẹ̀lú rẹ Ọlọ́run ni ọgbọ́n àti agbára:Òun ni ìmọ̀ àti òye.

14. Kíyèsí i, ó bì wó, a kò sì lè gberó mọ́;Ó ṣé ènìyàn mọ́, kò sì sí ìsísílẹ̀ kan.

15. Kíyèsí i, ó dá àwọn omi dúró,wọ́n sì gbẹ; Ó sì rán wọn jáde, wọ́n sì sẹ̀ bo ilẹ̀ ayé yípo.

16. Pẹ̀lú rẹ ni agbára àti ìṣẹ́gun;Ẹni tí ń sìnà àti ẹni tí ń mú ni sìnà, tirẹ̀ ni wọ́n ń ṣe.

17. Ó mú àwọn ìgbìmọ̀ lọ ní ìhòòhò,A sì sọ àwọn onídàájọ́ di òmùgọ̀.

18. Ó tú ìdè ọba,Ó sì fi mú àmùrè gbà wọ́n ní ọ̀já.

Ka pipe ipin Jóòbù 12