Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 12:1-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Jóòbù sì dáhùn, ó sì wí pé:

2. “Kò sí àní-àní níbẹ̀,ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni àwọn ènìyàn náà,ọgbọ́n yóò sì kú pẹ̀lú yín!

3. Ṣùgbọ́n èmi ní ìyè nínú gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin:èmi kò rẹ̀yìn sí i yín:àní, ta ni kò mọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí?

4. “Èmi dàbí ẹni tí a ń fi ṣe ẹlẹ́yà lọ́dọ̀ aládùúgbò rẹ̀,tí ó ké pe Ọlọ́run, tí ó sì dá a lóhùn:à ń fi olóòótọ́ ẹni-ìdúró-ṣinṣin rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà.

5. Ẹ̀gàn ni ẹni-ò-tòsì,tí ẹsẹ̀ rẹ múra tan láti yọ, nínú ìró ẹni tí ara rọ̀.

6. Àgọ́ àwọn ìgárá ń bẹ̀rù;àwọn tí ó sì ń mú Ọlọ́run bínú wà láìléwu,àwọn ẹni tí ó sì gbá òrìṣà mú ní ọwọ́ wọn.

7. “Ṣùgbọ́n nísínyìí bí àwọn ẹranko léèrè, wọn o kọ́ ọ ní ẹ̀kọ́,àti ẹyẹ ojú ọ̀run, wọn ó sì sọ fún ọ.

8. Tàbí ba ilẹ̀ àyé sọ̀rọ̀, yóò sì kọ́ ọ,àwọn ẹja inú òkun yóò sì sọ fún ọ.

9. Ta ni kò mọ̀ nínú gbogbo nǹkanwọ̀nyí pé, ọwọ́ Olúwa ni ó ṣe nǹkan yìí?

10. Ní ọwọ́ ẹni tí ẹ̀mí ohun alààyègbogbo gbé wà, Àti ẹ̀mí gbogbo aráyé.

11. Etí kì í dán ọ̀rọ̀ wò bí, Tàbí adùnẹnu kì í sì í tọ́ oúnjẹ rẹ̀ wò bí?

12. Àwọn arúgbó ni ọgbọ́n wà fún,Àti nínú gígùn ọjọ́ ni òye?

Ka pipe ipin Jóòbù 12