Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jóòbù 11:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ígbà náà ni Sófárì, ará Naamáa, dáhùn, ó sì wí pé:

2. “A ha lè ṣe kí a máa dáhùn sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀rọ̀?A ha lè fi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí da ènìyàn láre?

3. Ṣé àmọ̀tàn rẹ le mú ènìyàn pa ẹnu wọn mọ́ bí?Ṣé ẹnikẹ́ni kò ní bá ọ wí bí ìwọ bá yọ ṣùtì sí ni?

4. Ìwọ sáà ti wí fún Ọlọ́run pé,‘ìṣe mi jẹ́ aláìléérí, èmi sì mọ́ ní óju rẹ.’

5. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ìbá jẹ́ sọ̀rọ̀,kí ó sì ya ẹnu rẹ̀ sí ọ lára;

6. Kí ó sì fi àsírí ọgbọ́n hàn ọ́ pé, ó pọ̀ ju òye ènìyàn lọ;Nítorí náà, mọ̀ pé Ọlọ́run tigbàgbé àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kan.

Ka pipe ipin Jóòbù 11