1. “Ẹ̀yin ènìyàn Bẹ́ńjámínì, sá síbi ààbò!Ẹ sá kúrò ní Jérúsálẹ́mù,Ẹ fọn fèrè ní Tékóà!Kí ẹ gbé àmì sókè lórí Bẹti-Ákérémù!Nítorí àjálù farahàn láti àríwá,àní ìparun tí ó lágbára.
2. Èmi yóò pa ọmọbìnrin Síónì run,tí ó jẹ́ arẹwà àti ẹlẹgẹ́.
3. Olùṣọ́ àgùntàn pẹ̀lú agbo wọn yóò gbógun tì wọ́n.Wọn yóò pa àgọ́ yí wọn ká,olúkúlùkù yóò máa jẹ ní ilé rẹ̀.”