Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 52:30-34 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

30. Ní ọdún kẹtàlélógún ènìyànJúù tí Nebukadinésárì kó lọ sí ilẹ̀ àjòjì jẹ́ márùn ún.Gbogbo ènìyàn tí ó kó lápapọ̀ jẹ́ ẹgbẹ̀tàlélógún.

31. Ní ọdún kẹtàdín lógójì ti Jéhóáíkímù Ọba Júdà ni Efili-merodaki di Ọba Bábílónì. Ó tú Jéhóáíkímù Ọba Júdà sílẹ̀ nínú túbú ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n oṣù kéjìlá.

32. Ó ń sọ̀rọ̀ rere sí i, ó sì fún un ní ìjókòó ìgbéga, èyí tí ó ju ti àwọn Ọba yóòkù lọ tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ ní Bábílónì.

33. Nítorí náà, Jéhóáíkímù bọ́ aṣọ ẹ̀wọ̀n rẹ̀ ṣẹ́gbẹ̀ẹ́ fún ìyókù ọjọ́ ayé rẹ̀: Ó sì ń jẹun lórí àga Ọba.

34. Ní ojoojúmọ́ ni Ọba Bábílónì ń fún Jéhóáíkímù ní ìpín tirẹ̀ títí ọjọ́ ayé rẹ̀ tí ó fi kú.

Ka pipe ipin Jeremáyà 52