Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 50:33-39 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

33. Èyí ni ohun tí Olúwa alágbára sọ:“A pọ́n àwọn ènìyàn Ísírẹ́lìlójú àti àwọn ènìyàn Júdà pẹ̀lú.Gbogbo àwọn tí ó kó wọnnígbèkùn dì í mú ṣinṣinwọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálá.

34. Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára, Olúwa Ọlọ́run alágbára ni orúkọ rẹ̀.Yóò sì gbe ìjà wa jà,kí ó ba à lè mú wọn wá sinmí ní ilẹ̀ náà;àmọ́ kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Bábílónì.

35. “Idà lórí àwọn Bábílónì!”ni Olúwa wí,“lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Bábílónì,àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.

36. Idà lórí àwọn wòlíì èkéwọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun,wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.

37. Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́ ẹṣin rẹ̀àti àwọn àjòjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀.Wọn yóò di obìnrin.Idà lórí àwọn ohun ìṣura rẹ̀!

38. Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ.Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère,àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù.

39. “Nítorí náà àwọn ẹranko ijùpẹ̀lu ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀,abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀,a kì ó sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé,bẹ́ẹ̀ ni a kì ó ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran.

Ka pipe ipin Jeremáyà 50