1. “Lọ sókè àti sódò àwọn òpó Jérúsálẹ́mùWò yíká, kí o sì mọ̀,kí o sì wá kiriBí o bá le è rí ẹnìkan,tí ó jẹ́ olóòótọ́ àti olódodo,N ó dárí jìn ìlú yìí.
2. Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
3. Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n.Ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà.Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ,wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.