38. Ní gbogbo orílẹ̀ èdèMóábù àti ní ita kò síohun kan bí kò ṣe ọ̀fọ̀, nítorítí mo fọ́ Móábù bí a ti ń fọ́ohun elò tí kò wu ni,”ni Olúwa wí.
39. “Èéṣe tí ẹ fi fọ́ túútúú,tí ẹ sì fi ń pohùnréré ẹkún!Báwo ni Móábù ṣe yíẹ̀yìn padà ní ìtìjú!Móábù ti di ẹni ìtìjú àti ẹ̀gàn àtiìdààmú sí gbogbo àwọn tí ó yìí ká.”
40. Báyìí ni Olúwa wí:“Wò ó ẹyẹ idì náà ń fò bọ̀ nílẹ̀ó sì na ìyẹ́ rẹ̀ lórí Móábù.
41. Koríko kan yóò di kíkóàti àwọn ìlú olódì.Ní ọjọ́ náà ọkàn akọni Móábùyóò dàbí ọkàn obìnrin tí ó ń rọbí.
42. A ó pa Móábù run gẹ́gẹ́ bíorílẹ̀ èdè nítorípé ó gbéraga sí Olúwa.
43. Ẹ̀rù àti ọ̀fìn àti okùn dídèń dúró dè yín, ẹ̀yin ènìyàn Móábù,”ní Olúwa wí.
44. “Ẹnikẹ́ni tí ó bá sá fúnẹ̀rù yóò ṣubú sínú ọ̀fìnẹnikẹ́ni tí o bá jáde sítanínú ọ̀fìn ní à ó múnínú okùn dídè nítorí tíèmi yóò mú wá sóríMóábù àní ọdún Ìjìyà rẹ,”ní Olúwa wí.