Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 48:36-47 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

36. “Nítorí náà ọkàn mi rófún Móábù bí fèrè oróHíhárésétì ìṣúra ńlátí wọ́n kójọ ṣègbé.

37. Gbogbo orí mi ni ó pá,gbogbo irungbọ̀n ni a gé kúrò,gbogbo ọwọ́ ni a ṣá lọ́gbẹ́, àtiaṣọ ọ̀fọ̀ ní gbogbo ẹ̀gbẹ́.

38. Ní gbogbo orílẹ̀ èdèMóábù àti ní ita kò síohun kan bí kò ṣe ọ̀fọ̀, nítorítí mo fọ́ Móábù bí a ti ń fọ́ohun elò tí kò wu ni,”ni Olúwa wí.

39. “Èéṣe tí ẹ fi fọ́ túútúú,tí ẹ sì fi ń pohùnréré ẹkún!Báwo ni Móábù ṣe yíẹ̀yìn padà ní ìtìjú!Móábù ti di ẹni ìtìjú àti ẹ̀gàn àtiìdààmú sí gbogbo àwọn tí ó yìí ká.”

40. Báyìí ni Olúwa wí:“Wò ó ẹyẹ idì náà ń fò bọ̀ nílẹ̀ó sì na ìyẹ́ rẹ̀ lórí Móábù.

41. Koríko kan yóò di kíkóàti àwọn ìlú olódì.Ní ọjọ́ náà ọkàn akọni Móábùyóò dàbí ọkàn obìnrin tí ó ń rọbí.

42. A ó pa Móábù run gẹ́gẹ́ bíorílẹ̀ èdè nítorípé ó gbéraga sí Olúwa.

43. Ẹ̀rù àti ọ̀fìn àti okùn dídèń dúró dè yín, ẹ̀yin ènìyàn Móábù,”ní Olúwa wí.

44. “Ẹnikẹ́ni tí ó bá sá fúnẹ̀rù yóò ṣubú sínú ọ̀fìnẹnikẹ́ni tí o bá jáde sítanínú ọ̀fìn ní à ó múnínú okùn dídè nítorí tíèmi yóò mú wá sóríMóábù àní ọdún Ìjìyà rẹ,”ní Olúwa wí.

45. “Ní abẹ́ òjìji Hésíbónìàwọn tí ó sá dúró láìníolùrànlọ́wọ́ nítorí iná ti jáde wáláti Hésíbónì àti ọwọ́ ináláti àárin Síónì sì jó iwájú orí Móábù runàti agbárí àwọn ọmọ àlùfáà.

46. Ègbé ní fún ọ Móábù!Wọn yóò sì kó àwọn ọmọkùnrin yín lọ síilẹ̀ àjèjì àti àwọn ọmọbìnrin yín lọ sí ìgbékùn.

47. “Síbẹ̀, èmi yóò dá ìkólọMóábù padà ní ọjọ́ ìkẹyìn,”ni Olúwa wí.

Ka pipe ipin Jeremáyà 48