Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 48:32-43 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

32. Mo sunkún fún ọ bí Jásì ṣe sunkúnìwọ àjàrà Síbínà.Ẹ̀ka rẹ tẹ̀ títí dé òkun wọn,Ámónì,ajẹnirun ti kọlu èṣo rẹàti àwọn èṣo àjàrà rẹ.

33. Ayọ̀ àti ìdùnnú ti kúrònínú ọgbà àjàrà àti okoMóábù, mo dá ọwọ́ṣíṣàn ọtí wáìnì dúrólọ́dọ̀ olùfúnni; kò sí ẹni tíó ń tẹ̀ wọ́n pẹ̀lú igbe ayọ̀Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn kì í ṣe ti ayọ̀.

34. “Ohùn igbe wọn gòkè látiHésíbónì dé Élíà àti Jásìláti Sóà títí dé Hórónáímùàti Éjíbítì Sélíáyà, nítoríàwọn omi Nímírímù pẹ̀lú ti gbẹ

35. Ní ti Móábù ni èmi yóò ti fiòpin sí ẹni tí ó rúbọsí ibí gíga àti ẹni tí ń suntùràrí fún òrìṣà rẹ̀,”ni Olúwa wí.

36. “Nítorí náà ọkàn mi rófún Móábù bí fèrè oróHíhárésétì ìṣúra ńlátí wọ́n kójọ ṣègbé.

37. Gbogbo orí mi ni ó pá,gbogbo irungbọ̀n ni a gé kúrò,gbogbo ọwọ́ ni a ṣá lọ́gbẹ́, àtiaṣọ ọ̀fọ̀ ní gbogbo ẹ̀gbẹ́.

38. Ní gbogbo orílẹ̀ èdèMóábù àti ní ita kò síohun kan bí kò ṣe ọ̀fọ̀, nítorítí mo fọ́ Móábù bí a ti ń fọ́ohun elò tí kò wu ni,”ni Olúwa wí.

39. “Èéṣe tí ẹ fi fọ́ túútúú,tí ẹ sì fi ń pohùnréré ẹkún!Báwo ni Móábù ṣe yíẹ̀yìn padà ní ìtìjú!Móábù ti di ẹni ìtìjú àti ẹ̀gàn àtiìdààmú sí gbogbo àwọn tí ó yìí ká.”

40. Báyìí ni Olúwa wí:“Wò ó ẹyẹ idì náà ń fò bọ̀ nílẹ̀ó sì na ìyẹ́ rẹ̀ lórí Móábù.

41. Koríko kan yóò di kíkóàti àwọn ìlú olódì.Ní ọjọ́ náà ọkàn akọni Móábùyóò dàbí ọkàn obìnrin tí ó ń rọbí.

42. A ó pa Móábù run gẹ́gẹ́ bíorílẹ̀ èdè nítorípé ó gbéraga sí Olúwa.

43. Ẹ̀rù àti ọ̀fìn àti okùn dídèń dúró dè yín, ẹ̀yin ènìyàn Móábù,”ní Olúwa wí.

Ka pipe ipin Jeremáyà 48