1. Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Jeremáyà wòlíì sọ fún Bárúkì ọmọ Néríà ní ọdún kẹrin ti Jéhóíákímù ọmọ Jòsáyà Ọba Júdà. Lẹ́yìn tí Bárúkì ti kọ sínú ìwé kíká àwọn ọ̀rọ̀ tí Jeremáyà ti ń sọ:
2. “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Ísírẹ́lì sọ sí Bárúkì:
3. Ó wí pé, ‘Ègbé ni fún mi! Olúwa fi kún ìṣòro tí mo ní; mo di aláàbọ̀-ara pẹ̀lú ìrora àti àìní ìfọ̀kànbalẹ̀.’ ”