Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 36:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ọdún kẹrin Jéhóíákímù ọmọ Jòsáyà Ọba Júdà, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremáyà wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wí pé:

2. “Mú ìwé kíká fún ará rẹ, kí o sì kọ sínú rẹ̀ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti sọ nípa Ísírẹ́lì àti ti Júdà, àti sí gbogbo orílẹ̀ èdè láti ìgbà tí mo ti sọ fún ọ láti ọjọ́ Jòsáyà títí di òní.

3. Ó lè jẹ́ wí pé ilé Júdà yóò gbọ́ gbogbo ibi tí mo ti pinnu láti ṣe fún wọn; kí wọn kí ó sì yípadà, olúkúlùkù wọn kúrò ní ọ̀nà búburú rẹ̀. Kí èmi kí ó lè dárí àìṣedédé àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn jìn wọ́n.”

4. Nígbà náà ni Jeremáyà pe Bárúkì ọmọ Neráyà, ó sì sọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí Ọlọ́run báa sọ fún, Bárúkì sì kọ láti ẹnu Jeremáyà, gbogbo ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti sọ fún-un sórí ìwé kíká náà.

5. Nígbà náà ni Jeremáyà wí fún Bárúkì pé, “A ṣé mi mọ́! Èmi kò lè lọ sí ilé Olúwa.

6. Nítorí náà, ìwọ lọ sí ilé Olúwa ní ọjọ́ ààwẹ̀, kí o sì kà nínú ìwé kíkà náà ọ̀rọ̀ Olúwa tí ìwọ ti ẹnu mi kọ; ìwọ ó sì kà á ní etí gbogbo Júdà, tí wọ́n jáde wá láti ìlú wọn.

7. Ó lè jẹ́ pé, ẹbọ wọn yóò wá sí iwájú Olúwa, wọ́n ó sì yípadà kúrò ní ọ̀nà búburú wọn; nítorí pé títóbi ni ìbínú àti ìrunú tí Olúwa ti sọ sí àwọn ènìyàn yìí.”

Ka pipe ipin Jeremáyà 36