3. ‘Pè mí, èmi ó sì dá ọ lóhùn, èmi ó sì sọ ohun alágbára ńlá àti ọ̀pọ̀ ohun tí kò ṣe é wádìí tí ìwọ kò mọ̀ fún ọ.’
4. Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Ísírẹ́lì sọ nípa àwọn ilẹ̀ ìlú yìí àti ààfin àwọn Ọba Júdà tí ó ti wó lulẹ̀ nítorí àwọn ìdọ̀tí àti idà
5. Nínú ìjà pẹ̀lú Kálídéà: ‘Wọn yóò kún fún ọ̀pọ̀ òkú ọmọkùnrin tí èmi yóò pa nínú ìbínú àti nínú ìrunú mi. Èmi ó pa ojú mi mọ́ kúrò ní ìlú yìí nítorí gbogbo búburú wọn.
6. “ ‘Síbẹ̀, èmi ó mú okun àti ìwòsàn wá; èmi ó wo àwọn ènìyàn mi sàn. Èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó jẹ ìgbádùn ìyè lọ́pọ̀lọpọ̀ àti ìṣọ́.