1. Nígbà tí Jeremáyà wà nínú àgbàlá túbú, ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ̀ ọ́ wá lẹ́ẹ̀kejì:
2. “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹni tí ó dá ayé, Olúwa tí ó mọ ayé tí ó sì fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀, Olúwa ni orúkọ rẹ̀:
3. ‘Pè mí, èmi ó sì dá ọ lóhùn, èmi ó sì sọ ohun alágbára ńlá àti ọ̀pọ̀ ohun tí kò ṣe é wádìí tí ìwọ kò mọ̀ fún ọ.’
4. Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Ísírẹ́lì sọ nípa àwọn ilẹ̀ ìlú yìí àti ààfin àwọn Ọba Júdà tí ó ti wó lulẹ̀ nítorí àwọn ìdọ̀tí àti idà