Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 23:19-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Wò ó, afẹ́fẹ́ Olúwa yóò tú jádepẹ̀lú ìbínú àfẹ́yíká ìjì yóò fẹ́ síorí àwọn olùṣe búburú.

20. Ìbínú Olúwa kì yóò yẹ̀títí tí yóò sì fi mú èrò rẹ̀ ṣẹ,ní àìpẹ́ ọjọ́, yóò yé e yín yékéyéké.

21. Èmi kò rán àwọn wòlíì wọ̀nyísíbẹ̀ wọ́n lọ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọn.Èmi kò tilẹ̀ bá wọn sọ̀rọ̀,síbẹ̀ wọ́n sọ àṣọtẹ́lẹ̀,

22. Ṣùgbọ́n ìbáṣepọ̀ wọn dúró nínú ìgbìmọ̀ mi,wọn ì bá ti kéde ọ̀rọ̀ mi fún àwọn ènìyàn mi.Wọn ì bá ti wàásù ọ̀rọ̀ mi sí àwọn ènìyànwọn ìbá ti yípadà kúrò nínú ọ̀nààti ìṣe búburú wọn.

23. “Ǹjẹ́ Ọlọ́run tòsí nìkan ni Èmi bí?”ni Olúwa wí,“kì í sì í ṣe Ọlọ́run ọ̀nà jínjìn.

24. Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè sá pamọ́ sí ibi kọ́lọ́fín kan,kí èmi má ba a rí?”ni Olúwa wí.“Ǹjẹ́ èmi kò há a kún ọ̀run àti ayé bí?”ni Olúwa wí.

25. “Mo ti gbọ gbogbo ohun tí àwọn wòlíì èké tí ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ mi ń sọ. Wọ́n sọ wí pé, ‘Mo lá àlá! Mo lá àlá!’

26. Títí di ìgbà wo ni èyí yóò fi máa tẹ̀ṣíwájú ni ọkàn àwọn wòlíì èké wọ̀nyí tí wọ́n ń sọ ìtànjẹ ọkàn wọn?

Ka pipe ipin Jeremáyà 23