Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 20:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ìgbà tí àlùfáà Pásúrì ọmọkùnrin Ímímérì olórí àwọn ìjòyè Tẹ́ḿpìlì Olúwa gbọ́ tí Jeremáyà ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nǹkan wọ̀nyí.

2. Ó mú kí wọ́n lù ú, kí wọ́n sì fi sínú túbú tí ó wà ní òkè ẹnu ọ̀nà ti Bẹ́ńjámínì ní Tẹ́ḿpìlì Olúwa.

3. Ní ọjọ́ kejì tí Páṣúrì tú u sílẹ̀ nínú túbú, Jeremáyà sì sọ fún un wí pé, “orúkọ Olúwa kì í ṣe Páṣúrì fún ọ bí kò ṣe ohun ẹ̀rù.

4. Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa sọ. Èmi yóò mú ọ di ẹ̀rùjẹ̀jẹ̀ sí ara rẹ àti sí gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ. Ní ojú ara rẹ, ìwọ yóò sì rí tí wọ́n ṣubú nípa idà ọ̀tá wọn. Èmi yóò fi gbogbo àwọn ọ̀tá Júdà lé Ọba Bábílónì lọ́wọ́, òun yóò sì kó wọn lọ sí Bábílónì tàbí kí ó pa wọ́n.

Ka pipe ipin Jeremáyà 20