Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 2:10-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Rékọjá sí ẹkùn kan kítímì, kí osì wò ó, ránṣẹ́ sí kéda, kí o sìwò ó dáradára, wò ó kí ẹ sìwò ó bí irú nǹkan báyìí báwà níbẹ̀ rí?

11. Orílẹ̀ èdè kan há á pa Ọlọ́run rẹ̀ dà?(Síbẹ̀, wọn kì í ṣe iṣẹ́ Ọlọ́run)àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.

12. Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́sẹ̀ méjìkí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,”ni Olúwa wí.

13. “Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́sẹ̀, méjìWọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmiorísun omi ìyè, wọ́n sì tiwọ àmù, àmù fífọ́ tí kò lègba omi dúró.

14. Ísírẹ́lì há á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀ẹrú nípa ìbí? Kí ló há adé tí ó fi di ìkógun?

15. Àwọn kìnnìún ké ramúramúwọ́n sì ń bú mọ́ wọnwọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfòÌlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sìti di ìkọ̀sílẹ̀.

16. Bákan náà, àwọn ọkùnrinMémífísì àti Táfánésìwọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.

17. Ẹ̀yin kò há a ti fa èyí sóríara yín nípa kíkọ Ọlọ́run sílẹ̀nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?

Ka pipe ipin Jeremáyà 2