Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 17:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “Ẹ̀ṣẹ̀ Júdà ni a fi ṣóóṣó irin kọ sílẹ̀èyí tí ó hàn ketekete pẹ̀lú ẹnu ṣóróṣórósí oókan àyà wọn, àti lórí àwọn ìwotó wà lórí pẹpẹ wọn.

2. Kódà àwọn ọmọ wọn rántí pẹpẹàti òpó Áṣérà lẹ́bàá igi tí ó tẹ́ rẹrẹàti àwọn òkè gíga.

3. Àwọn òkè nínú ilẹ̀ àti àwọn ọrọ̀ rẹ̀àti ọlá rẹ̀ ni èmi yóò fi sílẹ̀ bí ìjẹpẹ̀lú àwọn ibi gíga, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ópọ̀ káàkiri orílẹ̀ èdè yín.

4. Láti ipaṣẹ̀ àìṣedéédé yín ni ẹ̀yinyóò ti sọ ogún tí mo fún un yín nù.Èmi yóò fi yín fún ọ̀tá yínbí ẹrú ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò mọ̀; nítoríẹ̀yin ti mú inú bí mi, èyí tí yóò sì wà títí ayé.”

5. Báyìí ni Olúwa wí:“Ègbé ni fún àwọn tí ó fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú ènìyàn,tí ó fi agbára rẹ̀ sínú ẹran ara,àti tí ọkàn rẹ̀ kò sí lọ́dọ̀ Olúwa

6. Yóò dàbí igbó tí ó wà ní ilẹ̀ aláìlọ́ràá,kò ní rí ire, nígbà tí ó bá dé yóòmáa gbé ní ibi ìyàngbẹ ilẹ̀ ihà,ní ilẹ̀ iyọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò gbé.

Ka pipe ipin Jeremáyà 17