Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 15:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé: “Kódà kí Mósè àti Sámúẹ́lì dúró níwájú mi, ọkàn mi kì yóò lọ sọ́dọ̀ àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Mú wọn kúrò níwájú mi! Jẹ́ kí wọn ó lọ!

2. Tí wọ́n bá sì bi ọ́ pé, ‘Níbo ni kí a lọ?’ Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí:“ ‘Àwọn tí a kọ ikú mọ́, sí ikú;àwọn tí a kọ idà mọ́, sí idà;àwọn tí a kọ ìyàn mọ́, sí ìyàn;àwọn tí a kọ ìgbékùn mọ́ sí ìgbékùn.’

3. “Èmi yóò rán oríṣìí ìparun mẹ́rin láti kọlù wọ́n,” ni Olúwa wí, “Idà láti pa, àwọn ajá láti wọ́ wọn lọ, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹranko orí ilẹ̀ láti jẹ àti láti parun.

4. N ó sọ wọ́n di ẹni ìkórìíra níwájú gbogbo ìjọba ayé torí ohun tí Mánásè ọmọ Heṣekáyà Ọba àwọn Júdà ṣe ní Jérúsálẹ́mù.

5. “Ta ni yóò ṣàánú rẹ, ìwọ Jérúsálẹ́mù?Ta ni yóò dárò rẹ?Ta ni yóò dúró béèrè àlàáfíà rẹ?

Ka pipe ipin Jeremáyà 15