Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 13:19-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Àwọn orílẹ̀ èdè tí ó wà ní Négéfì ni à ó tì pa,kò sì ní sí ẹnikẹ́ni láti sí wọn.Gbogbo Júdà ni a ó kó lọ sí ilẹ̀ ìgbèkùn,gbogbo wọn ni a ó kó lọ pátapáta.

20. Gbé ojú rẹ sókè,kí o sì wo àwọn tí ó ń bọ̀ láti àríwá.Níbo ni agbo ẹran tí a fi sí abẹ́ àkóso rẹ wà;àgùntàn tí ò ń mú yangàn.

21. Kí ni ìwọ yóò wí nígbà tí Olúwa bá dúró lórí rẹàwọn tí o mú bí ọ̀rẹ́ àtàtà.Ǹjẹ́ kò ní jẹ́ ìrora fún ọbí aboyún tó ń rọbí?

22. Tí o bá sì bi ara rẹ léèrè“Kí ni ìdí rẹ̀ tí èyí fi ṣẹlẹ̀ sí mi?”Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ tí o ṣẹ̀ni aṣọ rẹ fi fàyatí a sì ṣe é ní ìṣekúṣe.

23. Ǹjẹ́ Ètópíà le yí àwọ̀ rẹ̀ padà?Tàbí ẹkùn lè yí àwọ̀ rẹ̀ padà?Bí èyí kò ti lè rí bẹ́ẹ̀náà ni ẹ̀yin tí ìwà búburú bá ti mọ́ lára kò lè ṣe rere.

24. “N ó fọ́n ọn yín ká bí i ìyàngbòtí ẹ̀fúùfù ilẹ̀ aṣálẹ̀ ń fẹ́.

25. Èyí ni ìpín tìrẹ;tí mo ti fi sílẹ̀ fún ọ,”ni Olúwa wí,“nítorí ìwọ ti gbàgbé mití o sì gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọlọ́run àjèjì.

26. N ó sí aṣọ lójú rẹkí ẹ̀sín rẹ le hàn síta

Ka pipe ipin Jeremáyà 13