Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 11:20-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa àwọn ọmọ ogun,tí ó ń ṣe ìdájọ́ òdodo,tí ó ń ṣe àyẹ̀wò ẹ̀mí àti ọkàn,jẹ́ kí n rí ẹ̀san rẹ lórí wọn;nítorí ìwọ ni mo fi ọ̀rọ̀ mi lé lọ́wọ́.

21. “Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ọlọ́run sọ nípa àwọn arákùnrin Ánátótì tí wọ́n ń lépa ẹ̀mí rẹ̀, tí wọ́n ń wí pé, ‘Má ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ Olúwa, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìwọ ó kú láti ọwọ́ wa.’

22. Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ ogun sọ pé, ‘Èmi yóò fìyà jẹ wọ́n, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn yóò tipasẹ̀ idà kú, ìyàn yóò pa àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.

23. Kò ní ṣẹ́ku ohunkóhun sílẹ̀ fún wọn nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí àwọn ènìyàn Ánátótì ní ọdún ìjìyà wọn.’ ”

Ka pipe ipin Jeremáyà 11