Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 11:15-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. “Kí ni àyànfẹ́ mi ní í ṣe ní tẹ́ḿpìlì mi,bí ó ṣe ń hu oríṣiríṣi ìwà àrékérekè?Ǹjẹ́ ẹran tí a yà sọ́tọ̀ lè mú ìjìyà kúrò lórí rẹ̀?Nígbà tí ó bá ń ṣe iṣẹ́ ibi rẹ̀,inú rẹ̀ yóò máa dùn.”

16. Olúwa pè ọ́ ní igi ólífìpẹ̀lú èṣo rẹ tí ó dára ní ojú.Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìjì líleọ̀wọ́ iná ni yóò sun úntí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ yóò sì dá.

17. Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí ó dá ọ ti kéde ibi sí ọ, nítorí ilé Ísírẹ́lì àti Júdà ti ṣe ohun ibi, wọ́n sì ti mú inú bí mi, wọ́n ti ru ìbínú mi sókè nípa sísun tùràrí fún Báálì.

Ka pipe ipin Jeremáyà 11