Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 11:12-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Àwọn ìlú Júdà àti àwọn ará Jérúsálẹ́mù yóò lọ kégbe sí àwọn òrìṣà tí wọ́n ń sun tùràrí sí; àwọn òrìṣà náà kò ní ràn wọ́n lọ́wọ́ ní ìgbà tí ìpọ́nju òhún bá dé.

13. Bí iye àwọn ìlú yín ṣe pọ̀ tó náà ni àwọn òrìṣà yín. Ìwọ Júdà: àwọn pẹpẹ tí o ti pèsè fún jíjó tùràrí sí àwọn Báálì, òrìṣà yẹ̀yẹ́ sì pọ̀ bí iye òpópó tí ó wà ní Jérúsálẹ́mù.’

14. “Má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn, nítorí pé Èmi kò ní dẹtí sí wọn ní ìgbà ìpọ́njú.

15. “Kí ni àyànfẹ́ mi ní í ṣe ní tẹ́ḿpìlì mi,bí ó ṣe ń hu oríṣiríṣi ìwà àrékérekè?Ǹjẹ́ ẹran tí a yà sọ́tọ̀ lè mú ìjìyà kúrò lórí rẹ̀?Nígbà tí ó bá ń ṣe iṣẹ́ ibi rẹ̀,inú rẹ̀ yóò máa dùn.”

16. Olúwa pè ọ́ ní igi ólífìpẹ̀lú èṣo rẹ tí ó dára ní ojú.Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìjì líleọ̀wọ́ iná ni yóò sun úntí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ yóò sì dá.

17. Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí ó dá ọ ti kéde ibi sí ọ, nítorí ilé Ísírẹ́lì àti Júdà ti ṣe ohun ibi, wọ́n sì ti mú inú bí mi, wọ́n ti ru ìbínú mi sókè nípa sísun tùràrí fún Báálì.

18. Nítorí Ọlọ́run fi ọ̀tẹ̀ wọn hàn mí mo mọ̀ ọ́n; nítorí ní àsìkò náà ó fi ohun tí wọ́n ń ṣe hàn mí.

19. Mo ti dàbí ọ̀dọ́ àgùntàn jẹ́ẹ́jẹ́ tí a mú lọ fún pípa; N kò mọ̀ pé wọ́n ti gbìmọ̀ búburú sí mi wí pé:“Jẹ́ kí a run igi àti èso rẹ̀;jẹ́ kí a gé e kúrò ní orí ilẹ̀ alààyè,kí a mọ́ lè rántí orúkọ rẹ̀ mọ́.”

20. Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa àwọn ọmọ ogun,tí ó ń ṣe ìdájọ́ òdodo,tí ó ń ṣe àyẹ̀wò ẹ̀mí àti ọkàn,jẹ́ kí n rí ẹ̀san rẹ lórí wọn;nítorí ìwọ ni mo fi ọ̀rọ̀ mi lé lọ́wọ́.

Ka pipe ipin Jeremáyà 11