Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jeremáyà 1:1-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Èyí ni ọ̀rọ̀ Jeremáyà ọmọ Hílíkíyà ọ̀kan nínú àwọn àlùfáà ní Ánátótì ní gbígbé ilẹ̀ Bẹ́ńjámínì.

2. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá ní ọdún kẹtàlá ní àkókò ìjọba Jòṣáyà ọmọ Ámónì Ọba Júdà,

3. Àti títí dé àsìkò Jéhóákímù ọmọ Jòṣáyà Ọba Júdà, títí dé oṣù kaàrún ọdún kọkànlá Ṣedekáyà ọmọ Jòṣáyà Ọba Júdà, nígbà tí àwọn ará Jérúsálẹ́mù lọ sí ìgbèkùn.

4. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé,

5. Kí ó tó di pé mo dá ọ láti inú ni mo ti mọ̀ ọ́,kí ó sì tó di pé a bí ọ ni mo ti yà ọ́ sọ́tọ̀.Mo yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí wòlíì fún àwọn orílẹ̀ èdè.

6. Mo sọ pé Háà! Olúwa tí ó pọ̀ ní ipá, ọmọdé ni mí, èmi kò mọ bí a ṣe é sọ̀rọ̀.

7. Olúwa sọ fún mi pé, má ṣe sọ pé ọmọdé lásán ni mí. O gbọdọ̀ ní láti lọ sí ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tí mo rán ọ sí, kí o sì sọ ohun tí mo pa láṣẹ fún ọ.

8. Olúwa sì wí pé má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí tí èmi wà pẹ̀lú rẹ èmi ó sì gbà ọ́.

9. Olúwa sì na ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi kàn mí lẹ́nu, ó sì wí fún mi pé nísinsìnyìí mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí inú ẹnu rẹ

10. Wòó, mo yàn ọ́ lórí àwọn orílẹ̀ èdè àti ìjọba gbogbo láti fàtu, wó lulẹ̀, láti bàjẹ́, láti jágbà, láti má a kọ́, àti láti máa gbìn.

Ka pipe ipin Jeremáyà 1