Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 7:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Nóà pé, “Wọ inú ọkọ̀ lọ ìwọ àti gbogbo ìdílé rẹ, nítorí ìwọ nìkan ni mo rí bí olódodo nínú ìran yìí.

2. Mú méjeméje nínú àwọn ẹran tí ó mọ́, akọ àti abo, mú méjìméjì takọ tabo nínú àwọn ẹran aláìmọ́.

3. Sì mú méjeméje pẹ̀lú nínú onírúurú ẹyẹ takọ tabo ni kí o mú wọn, wọlé sínú ọkọ̀ pẹ̀lú rẹ, kí á baà lè pa wọ́n mọ́ láàyè ní gbogbo ayé.

4. Nítorí ní ọjọ́ méje sí ìhín, èmi yóò rọ òjò sórí ilẹ̀ fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, èmi yóò sì pa gbogbo ohun alààyè tí mo ti dá run, kúrò lórí ilẹ̀.”

5. Nóà sì ṣe ohun gbogbo tí Ọlọ́run pàṣẹ fún un.

6. Nóà jẹ́ ọmọ ẹgbẹ̀ta ọdún nígbà tí ìkún omi dé sórí ilẹ̀.

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 7