Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 6:16-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Ṣe òrùlé sí orí ọkọ̀ náà ní ìgbọ̀nwọ́ kan, sì ṣe ọkọ̀ náà ní alájà mẹ́ta, ipá kan ní ìṣàlẹ̀, ọ̀kan ní àárin àti ọ̀kan tí ó kù ní òkè, ẹ̀gbẹ́ ni kí ó ṣe ẹnu ọ̀nà ọkọ̀ náà sí.

17. Èmi yóò mú ìkún omi wá sí ayé láti pa gbogbo ohun ẹlẹ́mìí run, lábẹ́ ọ̀run. Gbogbo ẹ̀dá tí ó ní èémí ìyè ní inú. Gbogbo ohun tí ó wà nínú ayé yóò parun.

18. Ṣùgbọ́n èmi ó dá májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì wọ ọkọ̀, ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ pẹ̀lú aya rẹ.

19. Ìwọ yóò mú gbogbo ohun alààyè takọ tabo wá sí inú ọkọ̀ kí wọn le wà láàyè pẹ̀lú rẹ.

20. Mú onírúurú àwọn ẹyẹ, ẹranko àti àwọn ohun tí ń rákò ní méjìméjì kí a bá lè pa wọ́n mọ́ láàyè.

21. Mú onírúurú oúnjẹ wá sínú ọkọ̀ kí o pa wọ́n mọ́ fún jíjẹ gbogbo ẹ̀yin tí ẹ wà nínú ọkọ̀ àti ènìyàn àti ẹranko.”

22. Nóà sì ṣe ohun gbogbo bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún un.

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 6