Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 49:7-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Ìfibú ni ìbínú wọn nítorí tí ógbóná púpọ̀, àti fún ìrunú wọn nítorí tí ó kún fún ìkà.Èmi yóò tú wọn ká ní Jákọ́bù,èmi ó sì fọ́n wọn ká ní Ísírẹ́lì.

8. “Júdà, àwọn arákùnrin rẹ yóò yìn ọ,ọwọ́ rẹ yóò wà ní ọrùn àwọn ọ̀ta rẹ,àwọn ọmọkùnrin baba rẹ yóò foríbalẹ̀ fún ọ.

9. Ọmọ kìnnìún ni ọ́, ìwọ Júdà,o darí láti ìgbẹ́ ọdẹ, ọmọ mi.Bí i kìnnìún, o ba mọ́lẹ̀, o sì sùn sílẹ̀ bí i abo kìnnìún,Ta ni ó tó bẹ́ẹ̀, kí o lé e dìde?

10. Ọ̀pá oyè kì yóò kúrò ní Júdàbẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá-ìsàkóso kì yóò kúròláàrin ẹṣẹ̀ rẹ̀, títí tí ẹni tí ó ni í yóò fi dé,tí gbogbo àwọn orílẹ̀ èdè yóò máa wárí fún un.

11. Yóò má ṣo ọmọ ẹsin rẹ̀ mọ́ igi àjàrà àtiọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ mọ́ ẹ̀ka tí ó dára jù.Yóò fọ aṣọ rẹ̀ nínú wáìnì àti ẹ̀wùrẹ̀ nù nínú omi-pupa ti eṣo àjàrà (gíréèpù).

12. Ojú rẹ̀ yóò rẹ̀ dòdò ju wáìnì lọ,ẹyín rẹ yóò sì funfunu pẹ̀lú omi-ọyàn

13. “Ṣébúlúnì yóò máa gbé ní etí òkun,yóò sì jẹ́ èbúté fún ọkọ̀ ojú omi,agbégbé rẹ yóò tàn ká títí dé Ṣídónì.

14. “Ísákárì jẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ alágbáratí ó sùn sílẹ̀ láàrin àpò ẹrù méjì.

15. Nígbà tí ó bá rí bí ibi ìsinmi òun ti dára tó,àti bí ilẹ̀ rẹ̀ ti ní ìdẹ̀ra tó,yóò tẹ èjìká rẹ̀ ba láti ru àjàgà,yóò sì fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ ipá.

16. “Dánì yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀yà Ísírẹ́lì.

17. Dánì yóò jẹ́ ejo ni pópónààti paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà,tí ó bu ẹsin jẹ ní ẹṣẹ̀,kí ẹni tí n gùn-un bá à le è subú sẹ́yìn.

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 49