Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Jẹ́nẹ́sísì 47:7-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Nígbà náà ni Jósẹ́fù mú Jákọ́bù baba rẹ̀ wọlé wá sí iwájú Fáráò. Lẹ́yìn ìgbà tí Jákọ́bù súre fún Fáráò tán.

8. Fáráò béèrè pé, “Ọmọ ọdún mélòó ni ọ́?”

9. Jákọ́bù sì dá Fáráò lóhùn, “Ọdún ìrìn-àjò ayé mi jẹ́ àádóje (130), ọjọ́ mi kò pọ̀, ó sì kún fún wàhálà, ṣíbẹ̀ kò ì tí ì tó ti àwọn baba mi.”

10. Nígbà náà ni Jákọ́bù tún súre fún Fáráò, ó sì jáde lọ kúrò níwájú rẹ̀.

11. Joṣẹ́fù sì fi baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ sí ilẹ̀ Éjíbítì, ó sì fún wọn ní ohun-ìní ní ibi tí ó dára jù ní ilẹ̀ náà, ní agbégbé Ráméṣéṣì bí Fáráò ti pàṣẹ.

12. Jósẹ́fù sì pèṣè oúnjẹ fún baba rẹ̀ àti àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi iye àwọn ọmọ wọn.

13. Ṣùgbọ́n kò sí oúnjẹ ní gbogbo ilẹ̀ náà nítorí tí ìyàn náà mú púpọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ Éjíbítì àti ilẹ̀ Kénánì gbẹ nítorí ìyàn náà.

14. Jósẹ́fù gba gbogbo owó tí ó wà ní ilẹ̀ Éjíbítì àti Kénánì ní ìpààrọ̀ fún ti ọkà tí wọn ń rà, ó sì mú owó náà wá sí ààfin Fáráò.

15. Nígbà tí owó wọn tán pátapáta ní Éjíbítì àti Kénánì, gbogbo Éjíbítì wá bá Jósẹ́fù, wọ́n wí pé, “Fún wa ní oúnjẹ, èéṣe tí a ó fi kú ní ojú rẹ? Gbogbo owó wa ni a ti ná tan.”

16. Jósẹ́fù wí pé, “Ẹ mú àwọn ẹran-ọ̀sìn yín wá, èmi yóò fún un yín ní oúnjẹ ní ìpààrọ̀ fún ẹran-ọ̀sìn yín, níwọ̀n bí owó yín ti tan.”

Ka pipe ipin Jẹ́nẹ́sísì 47